Málákì 1:5-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Ẹ̀yin yóò sì fi ojú yín rí i, ẹ̀yin yóò sì wí pé, ‘Títóbi ni Olúwa, títóbi rẹ̀ tayọ kọjá agbègbè Ísírẹ́lì.’

6. “Ọmọ a máa bu ọ̀wọ̀ fún baba rẹ̀, ọmọ-ọ̀dọ̀ a sì máa bọlá fún ọ̀gá rẹ̀. Bí èmí bá jẹ́ baba ọ̀wọ̀ tí ó tọ́ sí mi dà? Bí èmi bá sì jẹ́ ọ̀gá ọlá, tí ó tọ́ sí mi dà?” ni Olúwa àwọn ọmọ ogun wí. “Ẹ̀yin ni, ẹ̀yin àlùfáà, ni ẹ ń gan orúkọ ọ̀ mi.“Ṣùgbọ́n ẹ̀yín béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe gan orúkọ ọ̀ rẹ?’

7. “Ẹ̀yín gbé oúnjẹ àìmọ́ sí orí pẹpẹ ẹ̀ mi.“Ẹ̀yín sì tún béèrè pé, ‘Báwo ni àwa ṣe ṣe àìmọ́ sí ọ?’“Nípa sísọ pé tábìlì Olúwa di ẹ̀gàn.

Málákì 1