27. Lóru àti ní ọ̀sán, bóyá ó sùn tàbí ó dìdè, irúgbìn náà hù jáde, ó sì dàgbà, òun kò sì mọ̀ bí ó ti ṣẹlẹ̀.
28. Nítorí tí ilẹ̀ kọ́kọ́ hù èso jáde fún ara rẹ̀, ó mú èéhù ewé jáde, èyí tí ó tẹ̀lé e ni orí ọkà, ní ìparí, ọkà náà gbó.
29. Nígbà tí èṣo bá gbó tan, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, òun a tẹ dòje bọ inú ọkà náà, ó sì kórè rẹ̀.”
30. Jésù sì tún wí pé, “Kí ni kí èmi fi ìjọba Ọlọ́run wé? Òwe wo ni kí èmi fi ṣe àkàwé rẹ̀?