Máàkù 4:11-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

11. Ó sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin ni a gbà láàyè láti mọ ohun ìjìnlẹ̀ nípa ìjọba Ọlọ́run. Èyí tí ó pamọ́ sí àwọn tí ó wà lẹ́yìn agbo ìjọba náà.

12. Bí ó tílẹ̀ jẹ́ wí pé,“ ‘wọn yóò rí i, wọn yóò sì gbọ́, kì yóò yé wọn,bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì yípadà sí Ọlọ́run.Tàbí kí a dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì wọ́n!’ ”

13. Ṣùgbọ́n Jésù wí fún wọn pé, “Bí òwe tí ó rọrùn yìí kò bá yé e yín? Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe mọ ìtumọ̀ àwọn mìíràn tí mo ń sọ fún un yín?

14. Afúrúgbìn ń fúnrúgbìn ọ̀rọ̀ náà.

15. Àwọn èṣo tó bọ́ sí ojú ọ̀nà líle, ni àwọn ọlọ́kan líle tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, lójúkan náà èṣù wá ó sì mú kí wọn gbàgbé ohun tí wọ́n ti gbọ́.

Máàkù 4