42. Wọ́n sì fún un ní ẹja tí a fi oyin sè.
43. Ó sì gbà á, ó jẹ ẹ́ lójú wọn.
44. Ó sì wí fún wọn pé, “Wọ̀nyí ni ọ̀rọ̀ tí mo sọ fún yín, nígbà tí èmí ti wà pẹ̀lú yín pé: A ní láti mú ohun gbogbo ṣẹ, tí a ti kọ nínú òfin Mósè, àti nínú ìwé àwọn wòlíì, àti nínú Sáàmù, nípasẹ̀ mi.”
45. Nígbà náà ni ó ṣí wọn níyè, kí ìwé mímọ́ lè yé wọn.