Lúùkù 13:31-35 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

31. Ní wákàtí kan náà, díẹ̀ nínú àwọn Farisí tọ̀ ọ́ wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Jáde, kí ìwọ sì lọ kúrò níhín-ín yìí: nítorí Hẹ́rọ́dù ń fẹ́ pa ọ́.”

32. Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ lọ, kí ẹ̀yin sì sọ fún kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ náà pé, ‘Kíyèsí i, èmi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde, èmi ń ṣe ìmúláradá lóní àti lọ́la, àti ní ijọ́ mẹ́ta èmi ó ṣe àṣepé.’

33. Ṣùgbọ́n èmi kò jẹ́ má rìn lóní, àti lọ́la, àti ní ọ̀túnla: kò lè jẹ́ bẹ́ẹ̀ pé wòlíì yóò ṣègbé lẹ́yìn odi Jerúsálémù.

34. “Jerúsálémù, Jerúsálémù, ìwọ tí o pa àwọn wòlíì, tí o sì sọ òkúta lu àwọn tí a rán sí ọ pa; nígbà mélòó ni èmi ń fẹ́ ràgà bo àwọn ọmọ rẹ, bí àgbébọ̀ ti í ràgà bo àwọn ọmọ rẹ̀ lábẹ́ apá rẹ̀, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fẹ́!

35. Sá wò ó, a fi ilé yín sílẹ̀ fún yín ní ahoro: lóòtóọ́ ni mo sì wí fún yín, Ẹ̀yin kì yóò sì rí mi títí yóò fi di àkókò tí ẹ̀yin ó wí pé, ‘Olùbùkún ni ẹni tí ó ń bọ̀ wá ní orúkọ Olúwa.’ ”

Lúùkù 13