Kólósè 4:15-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. Ẹ kí àwọn ará tí ó wà ńi Laodékíà, àti Nímífásì, àti ìjọ tí ó wà ní ilé rẹ̀.

16. Nígbà tí a bá sì ka ìwé yìí ní àárin yín tan, kí ẹ mú kí a kà á pẹ̀lú nínú ìjọ Laodékíà; ẹ̀yin pẹ̀lú sì ka èyí tí ó ti Laodékíà wá.

17. Kí ẹ sì wí fún Áríkípù pé, “Kíyèsi iṣẹ́ ìránṣẹ́ tí ìwọ ti gbà nínú Olúwa kí o sì ṣe é ní kíkún.”

18. Ìkíni láti ọwọ́ èmi Pọ́ọ̀lù. Ẹ máa ránti ìdè mi. Kí oore-ọ̀fẹ́ kí ó wà pẹ̀lú yín. Àmín. A kọ ọ́ láti Rómù lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ará Kólósè láti ọwọ́ Tíkíkù àti Ónísímù.

Kólósè 4