23. Nígbà náà ni Jóṣúà dáhùn wí pé, “Ẹ mú òrìṣà orílẹ̀-èdè mìíràn tí ń bẹ ní àárin yín kúrò, ki ẹ sì yí ọkàn yín padà sí Olúwa, Ọlọ́run Ísírẹ́lì.”
24. Àwọn ènìyàn náà sì wí fún Jóṣúà pé, “Olúwa Ọlọ́run nìkan ni àwa yóò máa sìn, òun nìkan ni àwa yóò máa ṣe ìgbọràn sí.”
25. Ní ọjọ́ náà Jóṣúà dá májẹ̀mu fún àwọn ènìyàn, ó sì fi òfin àti ìlànà fún wọn ní Sékémù.