32. Nígbà náà ni Fínéhásì ọmọ Élíásárì àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kénánì láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Réúbẹ́nì àti ẹ̀yà Gádì ní Gílíádì, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì lọ.
33. Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Réúbẹ́nì àti ẹ̀yà Gádì ń gbé.
34. Ẹ̀yà Réúbẹ́nì àti ẹ̀yà Gádì sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí: “Ẹ̀rí láàárin wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”