Jóṣúà 18:1-6 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì péjọ ní Ṣílò, wọ́n si kó Àgọ́ Ìpàdé ní ibẹ̀ Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,

2. ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Ísírẹ́lì tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.

3. Báyìí ni Jóṣúà sọ fún àwọn ọmọ Ísírẹ́lì: “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?

4. Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojúwo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.

5. Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Júdà dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúsù àti ilé Jósẹ́fù ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.

6. Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ gègé fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.

Jóṣúà 18