Jóòbù 6:17-25 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Nígbà kúgbà tí wọ́n bá gbóná wọn a sì yọ́ ṣànlọ,nígbà tí òòrùn bá mú, wọn a sì gbẹ kúrò ni ipò wọn.

18. Ìyà ọ̀nà wọn a sì yípadà sí apá kan,wọ́n gòkè sí ibi asán, wọ́n sì run.

19. Ẹgbẹ́ ogun Témà ń wòyeàwọn ọwọ́ àrò Sébà ń dúró dè wọ́n.

20. Wọ́n já lulẹ̀, nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lée;wọ́n débẹ̀, wọ́n sì dààmú.

21. Ǹjẹ́ nísinsìn yìí, ẹ̀yin dàbí wọn;ẹ̀yin rí ìrẹ̀sílẹ̀ mi àyà sì fò mí.

22. Èmi ó ha wí pé, ‘Ẹ mú ohun fún mi wá,tàbí pé ẹ fún mi ní ẹ̀bùn nínú ohun ìní yín?

23. Tàbí, ẹgbà mí lọ́wọ́ ọ̀tá ni,tàbí, ẹrà mí padà kúrò lọ́wọ́ alágbára nì.’?

24. “Ẹ kọ́ mi, èmi ó sì pa ẹnu mi mọ́kí ẹ sì mú mi wòye níbi tí mo gbé ti sìnà.

25. Wò ó! Bí ọ̀rọ̀ òtítọ́ ti lágbára tóṣùgbọ́n kí ni àròyé ìbàwí yín já sí?

Jóòbù 6