Jóòbù 39:4-24 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

4. Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́ndàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.

5. “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́?Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́,

6. Èyí tí mo fi ihà ṣe ilé fún, àtiilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀

7. Ó rẹ́rìnín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ niÒun kò sì gbọ́ igbe darandaran.

8. Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjókòó rẹ̀,Òun asì má a wá ewé tútù gbogbo rí.

9. “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí,ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?

10. Ìwọ le fi òkò tata de àgbáǹrérénínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa faìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?

11. Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀ lée nítorí agbára rẹ̀pọ̀ ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?

12. Ìwọ le gbẹ́kẹ̀ le pé, yóò mú èsooko rẹ̀ wá sílé, àti pé yóò sì kó ọ jọ sínu àká rẹ?

13. “Ìyẹ́ abo ògòǹgò ń fi ayọ̀ fì;Ṣùgbọ́n a kò le fi àká we ara wọn ní ìyẹ́ àti ìhùhù

14. Ó yé ẹ̀yìn rẹ̀ sílẹ̀ lórí ilẹ̀,a sì mú wọn gbóná nínú ekuru;

15. Tí ó sì gbàgbé pé, ẹ̀sẹ̀ lè tẹ̀ wọ́nfọ́, tàbí pé ẹranko ìgbẹ́ lè tẹ̀ wọ́n fọ́.

16. Kò ní àánú sí àwọn ọmọ rẹ̀ bíẹni pé wọn kì í ṣe tirẹ̀; asán ni iṣẹ́ rẹ̀, láì ní ìbẹ̀rù;

17. Nítorí pé Ọlọ́run kò fún-un ní ọgbọ́n,bẹ́ẹ̀ ni kò sì fi ìpín òye fún un.

18. Nígbà tí ó gbé ara sókè, ó ganẹṣin àti ẹlẹ́ṣin.

19. “Ìwọ ni ó fi agbára fún ẹṣin bí? tàbí ṣéÌwọ ni ó fi gọ̀gọ̀ wọ ọrùn rẹ̀ ní aṣọ?

20. Ìwọ le mú fò sókè bí ẹlẹ́ǹgà?Ògo èémí imú rẹ ní ẹ̀rù ńlá;

21. Ó fi ẹsẹ̀ halẹ̀ nínú àfonífojì, ó sì yọ̀ síagbára rẹ̀; ó lọ jáde láti pàdé àwọn ìhámọ́ra ogun.

22. Ó fi ojú kékeré wo ẹ̀rù, àyà kòsì fòó; bẹ́ẹ̀ ni kì í sì í padà ṣẹ́yìn kúrò lọ́wọ́ idà.

23. Lọ́dọ̀ rẹ ni apó-ọfà ń mìpẹ́kẹ́pẹ́kẹ́, àti ọ̀kọ̀ dídán àti àpáta.

24. Ó fi kíkorò ojú àti ìbínú ńlá gbéilẹ̀ mì, bẹ́ẹ̀ ni òun kò sì gbàá gbọ́ pé, ìró ipè ni.

Jóòbù 39