Jóòbù 39:3-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

3. Wọ́n tẹ ara wọn ba, wọ́n bí mọ,wọ́n sì mú ìkáànú wọn jáde.

4. Àwọn ọmọ wọn rí dáradára, wọ́ndàgbà nínú ọ̀dàn; wọ́n jáde lọ, wọn kò sì tún padà wá sọ́dọ̀ wọn.

5. “Ta ni ó jọ̀wọ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ oko lọ́wọ́?Tàbí ta ní ó tú ìdè kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ìgbẹ́,

6. Èyí tí mo fi ihà ṣe ilé fún, àtiilẹ̀ iyọ̀ ní ibùgbé rẹ̀

7. Ó rẹ́rìnín sí ariwo ìlú, bẹ́ẹ̀ niÒun kò sì gbọ́ igbe darandaran.

8. Orí àtòlé òkè ńlá ni ibùjókòó rẹ̀,Òun asì má a wá ewé tútù gbogbo rí.

9. “Àgbáǹréré ha jẹ́ sìn ọ́ bí? Tàbí,ó jẹ́ dúró ní ibùjẹ ẹran rẹ ní òru?

10. Ìwọ le fi òkò tata de àgbáǹrérénínú aporo? Tàbí ó jẹ́ máa faìtulẹ̀ nínú aporo oko tọ̀ ọ́ lẹ́yìn?

11. Ìwọ ó gbẹ́kẹ̀ lée nítorí agbára rẹ̀pọ̀ ìwọ ó sì fi iṣẹ́ rẹ lé e lọ́wọ́?

Jóòbù 39