Jóòbù 39:26-30 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

26. “Àwòdì ha máa ti ipa ọgbọ́n rẹ̀ fòsókè tí ó sì mọ ìyẹ́ apá rẹ̀ sí ìhà gúsù?

27. Idì ha máa fi àṣẹ rẹ̀ fò sókè kí ósì lọ tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ sí òkè gíga?

28. Ó ń gbé, ó sì ń wò ní orí àpáta,lórí pàlàpálá òkúta àti ibi orí òkè.

29. Láti ibẹ̀ lọ ni ó ti ń wá oúnjẹ́kiri, ojú rẹ̀ sì ríran rí òkè réré.

30. Àwọn ọmọ rẹ̀ pẹ̀lú a máa mu ẹ̀jẹ̀,níbi tí òkú bá gbé wà, níbẹ̀ ni òun wà pẹ̀lú.”

Jóòbù 39