Jóòbù 38:35-40 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

35. Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kíó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ósì wí fún wọn pé, àwa nìyí?

36. Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí ayétàbí tí ó fi òye sínú ọkàn?

37. Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọ̀sánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,

38. Nígbà tí erupẹ̀ di líle, àtiògúlùtú dípò?

39. “Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí?Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọ̀rọ̀ kìnnìún lọ́rùn,

40. Nígbà tí wọ́n bá ń mọ́lẹ̀ nínú ihòtí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?

Jóòbù 38