Jóòbù 33:23-27 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

23. “Bí oníṣẹ́ kan ba wà lọ́dọ̀ rẹ̀, ẹni tíń ṣe alágbàwí, ọ̀kan ninú ẹgbẹ̀rún láti fi ọ̀nà pípé hàn ni,

24. Nígbà náà ni ó ṣe oore ọ̀fẹ́ fún un ó sìwí pé, gbà á kúrò nínú ìlọ sínúìsà òkú èmi ti ràá pàdà;

25. Ara rẹ̀ yóò sì di ọ̀tun bí i ti ọmọkékeré, yóò sì tún padà sí ọjọ́ ìgbà èwe rẹ̀;

26. Ó gbàdúrà sọ́dọ̀ Ọlọ́run, òun sì seoju rere rẹ̀, o sì rí ojú rẹ̀ pẹ̀lúayọ̀, òhun o san òdodo rẹ̀ padà fún ènìyàn

27. Ó wá sọ́dọ̀ ènìyàn ó sì wí pé èmiṣẹ̀, kò sì sí èyí tí o tọ́, mo sì tiyí èyí tí ó tọ́ po, a kò sì san ẹ̀san rẹ̀ fún mi;

Jóòbù 33