Jóòbù 32:5-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

5. Nígbà tí Élíhù ríi pé ìdáhùn ọ̀rọ̀ kò sí ní ẹnu àwọn ọkùnrin mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí nígbà náà ni ó bínú.

6. Élíhù, ọmọ Bárákélì, ará Búsì,dáhùn ó sì wí pé: ọmọdé ní èmiàgbà sì ní ẹ̀yin; Ǹjẹ́ nítorí náàní mo dúró mo sì ń bẹ̀rù láti fiìmọ̀ mi hàn yin.

7. Èmi wí pé ọjọjọ́ ni ìbá sọ̀rọ̀, àtiọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún ní ìbá kọ́ ni ní ọgbọ́n.

8. Ṣùgbọ́n ẹ̀mi kan ní ó wà nínúènìyàn àti ìmísí Olódùmarè ní ì sì máa fún wọn ní òye.

9. Ènìyàn ńláńlá kì íṣe ọlọ́gbọ́n,Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbà ní òye ẹ̀tọ́ kò yé.

10. “Nítorí náà ní èmí ṣe wí pé: Ẹ dẹtí sílẹ̀ sí mi;èmí pẹ̀lú yóò fi ìmọ̀ mi hàn.

Jóòbù 32