Jóòbù 30:2-9 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

2. Kí ni ìwúlò agbára ọwọ́ wọn sími,níwọ̀n ìgbà tí agbára wọn ti fi wọ́n sílẹ̀?

3. Wọ́n rù nítorí àìní àti ìyànwọ́n ń rìn káàkiri ní ilẹ̀ gbígbẹní ibi ìkọsílẹ̀ ní òru.

4. Àwọn ẹni tí ń já ewé iyọ̀ ní ẹ̀báìgbẹ́; gbogbo igikígi ni ounjẹ jíjẹ wọn.

5. A lé wọn kúrò láàrin ènìyàn,àwọn ènìyàn sì pariwo lé wọn lórí bí ẹní pariwo lé olè lórí.

6. A mú wọn gbe inú pàlàpálá òkùtaàfonífojì, nínú ihò ilẹ̀ àti ti òkúta.

7. Wọ́n ń dún bí ẹranko ní àárinìgbẹ́, wọ́n kó ara wọn jọpọ̀ ní abẹ́ èṣìsì.

8. Àwọn ọmọ ẹni tí òye kò yé, àníàwọn ọmọ lásán, a sì lé wọn jáde kúrò ní orí ilẹ̀.

9. “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, àwọn ọmọ wọn ńfi mí ṣe ẹlẹ́yà nínú orin; àníèmi di ẹni ìsọ̀rọ̀ sí láàrin wọn.

Jóòbù 30