18. “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóòkú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí i yanrìn.
19. Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrìyóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
20. Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀mi, ọrun mi sì padà di titun ní ọwọ́ mi’
21. “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọna sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
22. Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
23. Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí péwọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò wọn a sìmu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀-kúrò.
24. Èmi sì rẹ́rìn ín sí wọn nígbà tí wọnkò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye síwọn.
25. Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sìjókòó bí olóyè wọn; mo jókòó bíọba ní àárin ológun rẹ̀; mo sìrí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń sọ̀fọ̀ nínú.