Jóòbù 18:10-15 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

10. A dẹkùn sílẹ̀ fún un lórí ilẹ̀, a sìwà ọ̀fìn fún un lojú ọ̀nà.

11. Ẹ̀rù ńlá yóò bà á ní ìhà gbogbo,yóò sì lé e dé ẹsẹ̀ rẹ̀.

12. Àìlera rẹ̀ yóò di pipa fún ebi,ìparun yóò dìde dúró sí i nígbà tí ó bá ṣubú.

13. Yóò jẹ ẹ̀yà ara rẹ̀; àkọ́bí ikú niyóò jẹ agbára rẹ̀ run.

14. A ó fà á tu kurò nínú àgọ́ tí ógbẹ́kẹ̀lé, a ó sì mú un tọ ọba ẹ̀rù ńlá nì lọ.

15. Yóò sì máa jókòó nínú àgọ́ rẹ̀èyí tí í ṣe tirẹ̀; ìmí ọjọ́ ni a ó fún káàkiri ibùgbé rẹ̀.

Jóòbù 18