1. “Lọ sókè àti sódò àwọn òpó Jérúsálẹ́mùWò yíká, kí o sì mọ̀,kí o sì wá kiriBí o bá le è rí ẹnìkan,tí ó jẹ́ olóòótọ́ àti olódodo,N ó dárí jìn ìlú yìí.
2. Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3. Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n.Ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà.Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ,wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4. Èmi sì rò pé, “talákà ni àwọn yìíwọn kò lóyenítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa,àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5. Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ,n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀;ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwaàti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.”Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́,wọ́n sì ti já ìdè.