Jeremáyà 48:33-36 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

33. Ayọ̀ àti ìdùnnú ti kúrònínú ọgbà àjàrà àti okoMóábù, mo dá ọwọ́ṣíṣàn ọtí wáìnì dúrólọ́dọ̀ olùfúnni; kò sí ẹni tíó ń tẹ̀ wọ́n pẹ̀lú igbe ayọ̀Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé wọn kì í ṣe ti ayọ̀.

34. “Ohùn igbe wọn gòkè látiHésíbónì dé Élíà àti Jásìláti Sóà títí dé Hórónáímùàti Éjíbítì Sélíáyà, nítoríàwọn omi Nímírímù pẹ̀lú ti gbẹ

35. Ní ti Móábù ni èmi yóò ti fiòpin sí ẹni tí ó rúbọsí ibí gíga àti ẹni tí ń suntùràrí fún òrìṣà rẹ̀,”ni Olúwa wí.

36. “Nítorí náà ọkàn mi rófún Móábù bí fèrè oróHíhárésétì ìṣúra ńlátí wọ́n kójọ ṣègbé.

Jeremáyà 48