Jeremáyà 48:16-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

16. “Ìṣubú Móábù súnmọ́;ìpọ́njú yóò dé kánkán.

17. Ẹ dárò fún, gbógbó ẹ̀yin tí ó yí i kágbogbo ẹ̀yin tí ẹ mọ bí ó ti ní òkìkí tó.Ẹ sọ pé, ‘Báwo ni ọ̀pá agbára rẹtítóbi tí ó sì lógo ṣe fọ́!’

18. “Sọ̀kalẹ̀ níbi ògo rẹ,kí o sì jókòó ní ilẹ̀ gbígbẹ,ẹ̀yin olùgbé ọmọbìnrin Díbónì,nítorí tí ẹni tí ó pa Móábù runyóò dojúkọ ọ́yóò sì pa àwọn ìlú olódi rẹ run.

19. Dúró lẹ́bàá ọ̀nà kí o sì wòran,ìwọ tí ń gbé ní Áróà.Bí ọkùnrin tí ó sálọ àti obìnrin tí ó ń sá àsálà‘kí ni ohun tí ó ṣẹlẹ̀?’

20. Ojú ti Móábù nítorí tí a wó o lulẹ̀,ẹ hu, sì kígbe síta!Ámónì kéde péa pa Móábù run.

21. Ìdájọ́ ti dé sí Pílátéùsórí Hólónì, Jáhásà àti Mẹ́fátì,

22. sórí Díbónì, Nébò àti Bẹti Díbílátaímù

23. sórí Kíríátaímù, Bẹti Gámù àti Bẹti Méónì,

Jeremáyà 48