Jeremáyà 33:15-19 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

15. “ ‘Ní ọjọ́ wọ̀n ọn nì àti ní àkókò náà,Èmi ó gbé olódodo dìde láti ẹ̀ka Dáfídì.Yóò ṣe ìdájọ́ àti ohun tí ó tọ́ ní ilẹ̀ náà.

16. Ní ọjọ́ wọ̀n ọn nì, Júdà yóò di ẹni ìgbàlà.Jérúsálẹ́mù yóò sì máa gbé láìséwuOrúkọ yìí ni a ó máa pè é Olúwa wa olódodo.’

17. Nítorí báyìí ni Olúwa wí: ‘Dáfídì kò ní kùnà láti rí ọkùnrin tí yóò jókòó lórí ìtẹ́ ní ilé Ísírẹ́lì.

18. Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àlùfáà tí ó jẹ́ ọmọ Léfì kò ní kùnà láti ní ọkùnrin kan tí ó dúró níwájú mi ní gbogbo ìgbà láti rú ẹbọ sísun; ẹbọ jíjẹ àti láti pèsè ìrúbọ.’ ”

19. Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremáyà wá wí pé:

Jeremáyà 33