Jẹ́nẹ́sísì 50:24-26 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Nígbà náà ni Jóṣẹ́fù wí fún àwọn arákùnrin rẹ̀ pé, “Mo ti fẹrẹ kú, ṣùgbọ́n dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, yóò sì mú-un yín jáde kúrò ní ilẹ̀ yìí lọ sí ilẹ̀ tí ó ti ṣèlérí ní ìbúra fún Ábúráhámù, Ísáákì àti Jákọ́bù.”

25. Jóṣẹ́fù sì mú kí àwọn ọmọ Ísírẹ́lì búra májẹ̀mu kan wí pé, “Dájúdájú Ọlọ́run yóò wá sí ìrànlọ́wọ́ yín, nígbà náà ni ẹ gbọdọ̀ kó egungun mi lọ́wọ́ kúrò ní ìhín.”

26. Báyìí ni Jóṣẹ́fù kú nígbà tí ó pé àádọ́fà (110) ọdún. Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n se òkú rẹ̀ lọ́jọ̀ tan, a gbé e sí inú pósí ní Éjíbítì.

Jẹ́nẹ́sísì 50