6. Ìyàn tí ó ti mú láti ọdún méjì sẹ́yìn yìí yóò tẹ̀ ṣíwájú fún ọdún márùn ún sí i nínú èyí tí ẹnikẹ́ni kò ní gbìn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ni kórè.
7. Ṣùgbọ́n Ọlọ́run rán mi ṣáájú yín sí ìhín láti da irú ọmọ yín sí fún-un yín lórí ilẹ̀ ayé àti láti fi ìgbàlà ńlá gba ẹ̀mí yín là.
8. “Nítorí náà kì í ṣe ẹ̀yin ni ó rán mi wá sí ìhín bí kò ṣe Ọlọ́run. Ó fi mí ṣe baba (Olùdámọ̀ràn) fún Fáráò, alákóso fún gbogbo ilé Fáráò àti alábojútó gbogbo ilẹ̀ Éjíbítì.