Jẹ́nẹ́sísì 38:24-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

24. Lẹ́yìn nǹkan bí oṣù mẹ́ta, wọn sọ fún Júdà pé, “Támárì aya ọmọ rẹ̀ ṣe àgbèrè, ó sì ti lóyún.”Júdà sì wí pé, “Ẹ mú un jáde, kí ẹ sì dá iná sun ún.”

25. Bí wọ́n sì ti ń mú un jáde, ó ránṣẹ́ sí baba ọkọ rẹ̀ pé, “Ọkùnrin tí ó ni àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó fún mi lóyún. Wò ó, bóyá o lè mọ ẹni tí ó ni èdìdì ìdámọ̀, okùn àti ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọ̀nyí.”

26. Júdà sì dá wọn mọ̀, ó sì wí pé, “O ṣe olódodo jù mí lọ, níwọ̀n ìgbà tí n kò fi fún Ṣélà ọmọ mi.” Kò sì bá a lò pọ̀ mọ́ láti ọjọ́ náà.

27. Nígbà tí àsìkò ìbímọ rẹ̀ tó. Ìbejì ọkùnrin ni ó bí.

28. Bí ó sì ti ń bímọ, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ náà na ọwọ́ jáde; agbẹ̀bí sì so okùn òdòdó mọ́ ọmọ náà ní ọrùn ọwọ́. Ó sì wí pé, “Èyí ni o kọ́kọ́ jáde.”

Jẹ́nẹ́sísì 38