Jẹ́nẹ́sísì 36:35-43 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

35. Nígbà tí Húṣámù kú, Hádádì ọmọ Bédádì tí ó ṣẹ́gun Mídíánì ní orílẹ̀ èdè Móábù sì jọba ní ipò rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Áfítì.

36. Lẹ́yìn ikú Ádádì, Ṣámílà tí ó wá láti Másírékà ni ó jọba lẹ́yìn rẹ̀.

37. Sámílà sì kú, Ṣáúlì ti Réhóbótì, létí odò sì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

38. Nígbà tí Sáúlì kú, Báálì-Hánánì ọmọ Ákíbórì jọba lẹ́yìn rẹ̀.

39. Nígbà tí Baali-Hánánì ọmọ Ákíbórì kú, Ádádì ni ó jọba lẹ́yìn rẹ̀. Orúkọ ìlú rẹ̀ ni Páù, Méhétà-bélì ọmọbìnrin Mátírédì àti ọmọ-ọmọ Mé-ṣáhábù ni ìyàwó rẹ̀.

40. Àwọn wọ̀nyí ni orúkọ àwọn ìjòyè tí ó ti ọ̀dọ̀ Ísọ̀ jáde wá, ní orúkọ ìdílé wọn, bí ìpínlẹ̀ wọn ti rí:Tínínà, Álífánì, Jététì.

41. Ohólíbámà, Élà, Pínónì,

42. Kénásì, Témáínì Míbísárì,

43. Mágídíélì, àti Írámù. Àwọn wọ̀nyí ni olóyè Édómù, gẹ́gẹ́ bí wọn ti tẹ̀dó sí ilẹ̀ tí wọ́n gbà.Èyí ni Ísọ̀ baba àwọn ará Édómù.

Jẹ́nẹ́sísì 36