28. Nígbà náà ni ọkùnrin náà wí pé, “Orúkọ rẹ kì yóò jẹ́ Jákọ́bù mọ́ bí kò ṣe Ísírẹ́lì, nítorí pé ìwọ ti bá Ọlọ́run àti ènìyàn jà, o sì borí.”
29. Jákọ́bù sì bẹ ọkùnrin náà pé, “Sọ orúkọ rẹ fún mi.”Ṣùgbọ́n ọkùnrin náà ṣáà dáhùn pé, “Èéṣe tí o n béèrè orúkọ mi?” Lẹ́yìn náà ó ṣúre fún Jákọ́bù níbẹ̀.
30. Jákọ́bù sì pe orúkọ ibẹ̀ ní Pẹ́núẹ́lì pé, “Mo rí Ọlọ́run ní ojúkojú, ṣíbẹ̀ a dá ẹ̀mí mi sí.”
31. Bí ó sì ti ń kọjá Pẹ́núẹ́lì, oòrùn ràn bá a, ó sì ń tiro nítorí itan rẹ̀.