Jẹ́nẹ́sísì 24:62-67 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

62. Ísáákì sì ń ti Bia-Lahai-Róì bọ, nítorí ìhà gúsù ni ó ń gbé.

63. Ísáákì sáà jáde lọ sí oko ni ìrọ̀lẹ́ láti ṣe àsàrò, bí ó sì ti gbé ojú sókè, ó rí àwọn ràkunmí tí ń bọ̀ wá.

64. Rèbékà pẹ̀lú sì gbójú sókè, ó sì rí Ísáákì. Ó sọ̀kalẹ̀ lórí ràkunmí,

65. Ó sì béèrè lọ́wọ́ ìránṣẹ́ náà wí pé, “Ta ni ọkùnrin tí ń bọ̀ wá pàdé wa láti inú oko?”Ìránṣẹ́ náà sì wí fun un pé, “Olúwa mi ni,” nítorí náà ni Rèbékà mú ìbòjú, ó sì bo ojú rẹ̀.

66. Nígbà náà ni ìránṣẹ́ náà ròyìn fún Ísáákì ohun gbogbo tí ó ti ṣe.

67. Nígbà náà ni Ísáákì mú Rèbékà wọ inú àgọ́ ọ ìyá rẹ̀, Ṣárà, ó sì di aya rẹ̀, ó sì fẹ́ràn rẹ̀; ó sì jẹ́ ìtùnú fún Ísáákì lẹ́yìn ikú ìyá rẹ̀.

Jẹ́nẹ́sísì 24