11. Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí dé Áṣíríà, níbi tí ó ti tẹ ìlú Nínéfè, Réhóbótì àti Kálà,
12. àti Résínì, tí ó wà ní àárin Nínéfè àti Kálà, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
13. Mísíráímù ni baba ńlá àwọn aráLúdì, Ánámì, Léhábì, Náfítúhímù.
14. Pátírúsímù, Kásílúhímù (èyí tí í ṣe baba ńlá àwọn Fílístínì) àti Káfítórímù.
15. Kénánì ni baba àwọn aráSídónì (èyi ni àkọ́bí rẹ̀), àti àwọn ara Hítì.