29. Àwọn enìyàn ilẹ̀ náà, tí lo ìwà ìnínilára, wọn sì já olè, wọn sì ni àwọn tálákà àti aláìní lára; nítòótọ́, wọn tí ní àlejò lára láìnídí. Kò sì sí ìdájọ́ òdodó.
30. “Èmi si wá ẹnìkan láàrin wọn, tí ìbá tún odi náà mọ́, tí ìbá dúró ní ibi tí ó ya náà níwájú mi fún ilẹ̀ náà, kí èmi má báà parun: ṣùgbọ́n èmi kò rí ẹnìkan.
31. Nítorí náà ni mo ṣe ma da ìbínú mi sí wọn lórí; máa fí iná ìbínú mi run wọn: mo si ma fi ọ̀nà wọn gbẹ̀san lórí ara wọn, ní Olúwa Ọlọ́run wí.”