21. “Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí: Báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jérúsálẹ́mù-èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-àrùn-láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!
22. Síbẹ̀, yóò ṣẹ́kù àwọn díẹ̀-àwọn ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin tí a ó kó jáde nínú rẹ̀. Wọn yóò wá bá yin, ẹ ó rí ìwà àti ìṣe wọn, nígbà náà ni ẹ ó rí ìtùnú nípa àjálù tí mo mú wá sórí Jérúsálẹ́mù—àní gbogbo àjálù ní mo ti mú wá sórí rẹ̀.
23. Nígbà tí ẹ bá rí ìwà àti ìṣe wọn, a ó tù yín nínú, nítorí pé ẹ ó mọ̀ pé n kò ṣe nǹkan kan láì nídìí, ni Olúwa Ọlọ́run wí.”