19. “Tàbí bí mo rán àjàkálẹ̀-àrùn si ilẹ̀ náà, ti mo si da ìrunu mi lé e lórí pẹ̀lú ẹ̀jẹ̀, láti gé ènìyàn àti ẹranko kúrò nínú rẹ̀,
20. bo tilẹ̀ jẹ́ pé Nóà, Dáníẹ́lì àti Jóòbù wà nínú rẹ, bí mo ti wà láàyè ni Olúwa Ọlọ́run wí wọn kò le gba ọmọkùnrin tàbí ọmọbìnrin wọn lá. Ara wọn nìkan ni ìwà òdodo wọn lè gbà là.
21. “Nítorí báyìí ni Olúwa Ọlọ́run wí: Báwo ni yóò ti burú tó nígbà tí mo bá rán ìdájọ́ kíkan mi mẹ́rin sórí Jérúsálẹ́mù-èyí ni idà àti ìyàn, ẹranko búburú àti àjàkálẹ̀-àrùn-láti pa àwọn ènìyàn àti ẹranko inú rẹ̀!