Ísíkẹ́lì 10:1-4 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Mo sì wò ó, mo rí ohun kan tó dàbí òkúta sáfírè nínú òfuurufú tó wà lókè orí kérúbù, ìrísí ohun yìí sì dàbí ìtẹ́.

2. Olúwa sì sọ fún ọkùnrin tó wọ aṣọ funfun pé, “Lọ sí àárin àwọn kẹ̀kẹ́ tó wà lábẹ́ kérúbù. Bu ẹyin iná tó kúnwọ́ rẹ láàrin kérúbù, kí o sì fọ́n-ọn sórí ìlú náà.” Ó sì lọ lóju mi.

3. Àwọn kérúbù dúró sí apá gúúsù tẹ́ḿpìlì nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ìkùukùu sì bo inú àgbàlá.

4. Ògo Olúwa sì kúrò lórí àwọn kérúbù, ó bọ́ sí ibi ìloro tẹ́ḿpìlì. Ìkùukùu sì bo inú tẹ́ḿpìlì, àgbàlá sì kún fún ìmọ́lẹ̀ àti ògo Olúwa.

Ísíkẹ́lì 10