16. “Yóò si ṣe ní ọjọ́ náàÌwọ yóò pè mí ní ‘Ọkọ mi’;Ìwọ kò sì ní pè mí ní ‘olúwa à mi mọ́,’ni Olúwa wí.
17. Èmi yóò mú orúkọ, àwọn òrìṣà Báálì kúrò lẹ́nu rẹ̀;ìwọ kò sì ní rí orúkọ òrìṣà Báálì pè mọ́
18. Ní ọjọ́ náà, èmi yóò ṣe májẹ̀múfún wọn àti àwọn ẹranko ìgbẹ́ àti ẹyẹ ojú ọ̀run àtiàwọn ẹ̀dá tí ń rìn lórí ilẹ̀.Kí wọn má bà á bẹ̀rù ara wọn mọ́Ọrun, idà àti ogun jíjà ni èmi ó parun ní ilẹ̀ náàkí gbogbo ènìyàn bá a lè wà ní àìléwu.
19. Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi títí láé.Èmi ó fẹ́ ọ ní ìwà òdodo àtiòtítọ́, ní ìfẹ́ àti àánú.
20. Èmi yóò fẹ́ ọ fún ara mi ní ìsòtítọ́ìwọ yóò sì mọ Olúwa
21. “Èmi yóò sì dáhùn ní ọjọ́ náà”ni Olúwa wí.“Èmi yóò dá àwọn ọ̀run lóhùnàwọn ọ̀run yóò sì dá ilẹ̀ lóhùn;