Ẹ́sítà 9:1-7 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. Ní ọjọ́ kẹtàlá oṣù kejìlá, oṣù Ádárì, tí ó yẹ kí a mú àṣẹ tí ọba pa wá sí ìmúṣẹ. Ní ọjọ́ yìí ni ọ̀tá àwọn Júù rò pé àwọn yóò borí i wọn, ṣùgbọ́n nísinsin yìí a ti yìí padà, àwọn Júù sì na ọwọ́ agbára tó ga lórí àwọn tí ó kóòríra wọn.

2. Àwọn Júù pé jọ ní àwọn ìlú u wọn ní gbogbo agbégbé ọba Ṣéríṣésì láti kọlu àwọn tó ń wá ìparun wọn. Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó lè dojú kọ wọ́n, nítorí gbogbo àwọn ènìyàn ìlú tó kù ń bẹ̀rù u wọn.

3. Gbogbo àwọn ọlọ́lá ìgbéríko, àwọn alákòóso, àwọn baálẹ̀ àti àwọn onídàájọ́ ọba ran àwọn Júù lọ́wọ́, nítorí wọ́n bẹ̀rù u Módékáì.

4. Módékáì sì jẹ́ ẹni pàtàkì ní ààfin, òkìkíi rẹ̀ sì tàn jákè jádò àwọn ìgbéríko, ó sì ní agbára kún agbára.

5. Àwọn Júù sì gé gbogbo àwọn ọ̀tá a wọn lulẹ̀ pẹ̀lú idà, wọ́n pa wọ́n, wọ́n sì run wọ́n, wọ́n sì ṣe ohun tí ó wù wọ́n sí àwọn tí ó kóòríra wọn.

6. Ní ilé ìṣọ́ ti Ṣúṣà, àwọn Júù pa ẹ̀ẹ́dẹ́gbẹ̀ta ọkùnrin run

7. Wọ́n sì tún pa parisánídátà, Dálífónì, Ásípátà,

Ẹ́sítà 9