3. Nígbà tí mo gbọ́ èyí, mo fa àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi ya, mo ja irun orí àti irungbọ̀n mi, mo sì jókòó ní ìbànújẹ́.
4. Nígbà náà ni gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù ọ̀rọ̀ Ọlọ́run Ísírẹ́lì kó ara wọn jọ yí mi ká nítorí àìsòótọ́ àwọn ìgbékùn yìí. Èmi sì jókòó níbẹ̀ ní ìbànújẹ́ títí di àkókò ìrúbọ àṣálẹ̀.
5. Ní ìgbà tí o di àkókò ìrúbọ àṣálẹ̀, mo dìde kúrò nínú ìrẹ̀wẹ̀sì ọkàn mi, pẹ̀lú àwọ̀tẹ́lẹ̀ àti agbádá mi yíya ní ọrùn mi, mo kúnlẹ̀ lórí eékún mi méjèèjì, mo sì tẹ́ ọwọ́ mi méjèèjì sí Olúwa Ọlọ́run mi.
6. Mo sì gbàdúrà:Ọlọ́run mi, ojú tì mí gidigidi kò sì yá mi lórí láti gbé ojú mi sókè sí ọ, Ọlọ́run mi, nítorí ẹṣẹ̀ wá ga ju orí wa lọ, àwọn àìṣedéédéé wa sì ga kan àwọn ọ̀run.