Ẹ́sírà 4:17-23 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

17. Ọba fi èsì yìí ránṣẹ́ padà:Sí Réhúmì balógun, Ṣímíṣáì akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn yóòkù tí ń gbé ní Samáríà àti ní òpópónà Yúfúrátè:Ìkíní.

18. A ti ka ìwé tí ẹ fi ránṣẹ́ sí wa, a sì ti túmọ̀ rẹ̀ níwájú mi.

19. Mo pa àṣẹ, a sì ṣe ìwádìí, nínú ìtàn ọjọ́ pípẹ́ àti ti ìsinsinyìí ti ìṣọ̀tẹ̀ sí àwọn ọba pẹ̀lú, ó sì jẹ́ ibi ìṣọ̀tẹ̀ àti ìrúkèrúdò.

20. Jérúsálẹ́mù ti ní àwọn ọba alágbára tí ń jọba lórí gbogbo àwọn agbégbé Yúfúrátè, àti àwọn owó orí, owó òde àti owó ibodè sì ni wọ́n ń san fún wọn.

21. Nísinsìn yìí pa àṣẹ fún àwọn ọkùnrin yìí láti dá iṣẹ́ dúró, kí a má ṣe tún ìlú náà kọ títí èmi yóò fi pàṣẹ.

22. Ẹ ṣọ́ra kí ẹ má ṣe àìkọbi-ara sí ọ̀rọ̀ yìí. Èéṣe tí ìbàjẹ́ yóò fi pọ̀ sí i, sí ìpalára àwọn ọba?

23. Ní kété tí a ka ẹ̀dà ìwé ọba Aritaṣéṣéṣì sí Réhúmì àti Ṣímíṣáì akọ̀wé àti àwọn ẹlẹgbẹ́ ẹ wọn, wọ́n yára lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn Júù ní Jérúsálẹ́mù pẹ̀lú, wọ́n fi agbára mú wọn láti dáwọ́ dúró.

Ẹ́sírà 4