Ẹkún Jeremáyà 5:9-18 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

9. Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wanítorí idà tí ó wà ní ihà.

10. Ẹran ara wa gbóná bí ààrò,ebi sì yó wa bí àárẹ̀.

11. Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lò pọ̀ ní Síónì,àti àwọn wúndíá wa ní ìlú Júdà.

12. Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di ṣíṣo sókè ní ọwọ́ wọn;kò sí ìbọ̀wọ̀ fágbà mọ́.

13. Àwọn ọdọ́mọkùnrin wa ru òkúta;àwọn ọmọkùnrin sì ńṣsàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.

14. Àwọn àgbààgbà ti lọ kúrò ní ẹnu bodè ìlú;àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn

15. Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa;ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.

16. Adé ti sí kúrò ní orí waÈgbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.

17. Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa,nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.

18. Fún òkè Síónì tí ó ti di ahorolórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.

Ẹkún Jeremáyà 5