Ékísódù 7:6-10 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

6. Mósè àti Árónì sì ṣe gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ́ fún wọn.

7. Mósè jẹ́ ọmọ ọgọ́rin ọdún (80) Árónì sì jẹ́ ọmọ ọdún mẹ́talélọ́gọ́rin (83) ni ìgbà tí wọ́n bá Fáráò sọ̀rọ̀.

8. Olúwa sọ fún Mósè àti Árónì,

9. “Ní ìgbà tí Fáráò bá sọ fún un yín pé, ‘Ẹ ṣe iṣẹ́ ìyanu kan,’ sọ fún Árónì ní ìgbà náà pé, ‘Mú ọ̀pá rẹ kí ó sì sọ ọ́ sílẹ̀ níwájú Fáráò,’ yóò sì di ejò.”

10. Nígbà náà ni Mósè àti Árónì tọ Fáráò lọ, wọ́n sì ṣe bí Olúwa ti pàṣẹ fún wọn, Árónì ju ọ̀pá rẹ̀ sílẹ̀ ní ìwájú Fáráò àti àwọn ìjòyè rẹ̀, ọ̀pá náà sì di ejò.

Ékísódù 7