3. Ẹ má se dáná kankan ní ibùgbé yín ní ọjọ́ ìsinmi.”
4. Mósè sọ fún gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Ísírẹ́lì pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa pa láṣẹ:
5. Láti inú ohun tí ẹ ni ni kí ẹ ti mú ọrẹ fún Olúwa. Ẹnikẹ́ni tí ọ́ bá fẹ́ ni kí ó mú ọrẹ fún Olúwa ní ti wúrà, fàdákà àti idẹ;
6. aṣọ aláró, elésèé àlùkò, òdòdó àti ọ̀gbọ̀ dáradára; àti irun ewúrẹ́;