26. “Mú èyí tí ó dára nínú àkọ́so èso ilẹ̀ rẹ wá sí ilé Olúwa Ọlọ́run rẹ.“Má ṣe ṣe ọmọ ewúrẹ́ nínú wàrà ìyá rẹ̀.”
27. Olúwa sì wí fún Mósè pé, “Kọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí sílẹ̀, nítorí nípa àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí ni èmi bá ìwọ àti Ísírẹ́lì dá májẹ̀mú.”
28. Mósè wà níbẹ̀ pẹ̀lú Olúwa fún ogójì ọ̀sán àti ogójì òru (40) láì jẹ oúnjẹ tàbí mu omi. Ó sì kọ ọ̀rọ̀ májẹ̀mú náà òfin mẹ́wàá sára wàláà.