Ékísódù 29:1-5 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

1. “Èyí ni ohun tí ìwọ yóò ṣe láti yà wọ́n sí mímọ́, nítorí kí wọn lè máa àti láti máa sìn se àlùfáà fún mi: Mú ọ̀dọ́ akọ màlúù kan àti àgbò méjì tí kò ní àbùkù.

2. Láti ara ìyẹ̀fun aláìwú dídùn, ṣe àkàrà àti àkàrà tí a pò pẹ̀lú òróró, àti àkàrà fẹ́lẹ́fẹ́lẹ́ aláìwú tí a da òróró sí.

3. Ìwọ yóò sì kó wọn sínú àpẹ̀rẹ̀ kan, ìwọ yóò sì mú wọn wà nínú apẹ̀rẹ̀ náà—papọ̀ pẹ̀lú akọ màlúù àti àgbò méjì náà.

4. Nígbà náà ni ìwò yóò mú Árónì àti àwọn ọmọ rẹ̀ wá sí ẹnu ọ̀nà àgọ́ àjọ, ìwọ yóò sì fi omi wẹ̀ wọ́n.

5. Ìwọ yóò sì fi ẹ̀wù àwọ̀tẹ́lẹ̀ wọ Árónì, àti aṣọ ìgúnwà éfódì, àti éfódì, àti ìgbàyà, kí ó sì fi onírúurú-ọnà ọ̀já ẹ̀wù èfòdì dìí.

Ékísódù 29