1. Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Mósè pé, “Lọ sí ọ̀dọ̀ Fáráò, mo ti ṣé ọkàn Fáráò le àti ọkàn àwọn ìjòyè rẹ̀, kí èmi kí o ba le ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu mi láàrin wọn.
2. Kí ẹ̀yin ki ó le sọ fún àwọn ọmọ yin àti àwọn ọmọ ọmọ yín; Bí mo ti jẹ àwọn ará Éjíbítì níyà àti bí mo ti ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu láàrin wọn. Kí ìwọ ba á le mọ̀ pé èmi ni Olúwa.”
3. Nígbà náà ni Mósè àti Árónì tọ Fáráò lọ, ti wọn sí wí fún pé, “Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn Hébérù sọ: ‘Yóò ti pẹ́ to ti ìwọ yóò kọ̀ láti tẹrí ara rẹ ba ní iwájú mi?