Àwọn Hébérù 7:27-28 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

27. Ẹni tí kò ní láti máa rúbọ lójojúmọ́, bí àwọn olórí àlùfáà, fún ẹ̀ṣẹ̀ ti ara rẹ̀ náà, àti lẹ̀yìn náà fún tí àwọn ènìyàn; nítorí èyí ni tí ó ṣe lẹ́ẹ̀kan ṣoṣo, nígbà tí ó fi ara rẹ̀ rúbọ.

28. Nítorí pé òfin a máa fi àwọn ènìyàn tí ó ní àìlera jẹ olórí àlùfáà; ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ ti ìbúra, tí ó ṣe lẹ̀yín òfin, ó fi ọmọ jẹ; ẹni tí a sọ di pípé títí láé.

Àwọn Hébérù 7