Ámósì 2:8-12 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

8. Wọ́n dùbúlẹ̀ lẹ́bá a pẹpẹLórí aṣọ tí wọ́n ti jẹ́jẹ̀ẹ́ní ilé òrìṣà wọnwọ́n sì mu ọtí tí wọ́n san fún ìtanràn.

9. “Mo pa àwọn ará Ámórì run níwájú wọngíga ẹni tí ó dàbí igi Kédárì.Òun sì le koko bí igi Óákùmo pa èso rẹ̀ run láti òkè wáàti egbò rẹ̀ láti ìṣàlẹ̀ wá.

10. “Èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Éjíbítì wá,mo sì sìn yín la ihà já ní ogójì ọdúnláti fi ilẹ̀ àwọn ará Ámórì fún un yín.

11. Èmi sì tún gbé àwọn wòlíì dìde láàárin àwọn ọmọ yínàti láàárin àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin yín láti jẹ Násárátìèyí kò ha jẹ́ òtítọ́ bí ará Ísírẹ́lì?”ni Olúwa wí.

12. “Ṣùgbọ́n ẹ̀yin fún àwọn Násárátì ní ọtí muẸ sì pàṣẹ fún àwọn wòlíì kí wọ́n má ṣe sọ tẹ́lẹ̀.

Ámósì 2