Ámósì 1:7-11 Bíbélì Mímọ́ ní Èdè Yorùbá Òde Òní (BMY)

7. Èmi yóò rán iná sí ara odi Gásàtí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run

8. Èmi yóò ké àwọn olùgbé Ásódì kúrò.Àti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé ní Ákélónì mú.Èmi yóò yí ọwọ́ mi sí Ékírónìtítí tí ìyókù Fílístínì yóò fi ṣègbé,”ni Olúwa Ọlọ́run wí.

9. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta ti Tírèàní nítorí mẹ́rin, Èmi kì yóò yí ìpinnu ìjìyà mi padà.Nítorí wọ́n ta gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ìgbékùn fún ÉdómùWọn kò sì nán-án-ní májẹ̀mú ọbàkan,

10. Èmi yóò rán iná sí ara odi TírèTí yóò jó gbogbo àwọn ààfin rẹ̀ run.”

11. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Édómù,àní nítorí mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàNítorí òhun fi idà lépa arákùnrin rẹ̀,Ó sì gbé gbogbo àánú sọnùìbínú rẹ̀ sì ń faniya títíó sì pa ìbínú rẹ̀ bí èéfín mọ́

Ámósì 1