1. Àwọn ọ̀rọ̀ Ámósì, ọ̀kan lára àwọn olùsọ́ àgùntàn Tékóà; ohun tí o rí nípa Ísírẹ́lì ní ọdun méjì ṣáàjú ilẹ̀ riri, nígbà tí Úsáyà ọba Júdà àti Jéróbóámù ọmọ Jéóhásì jẹ́ ọba ní ilẹ̀ Ísírẹ́lì.
2. Ó wí pé:“Olúwa yóò bú jáde láti Síóníohùn rẹ̀ yóò sì sán bí àrá láti Jérúsálẹ́mù wá;Ibùgbé àwọn olùṣọ́ àgùntàn yóò sì ṣọ̀fọ̀,Orí-òkè Kámẹ́lì yóò sì rọ.”
3. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta tí Dámásíkù,àní fún mẹ́rin, Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padaNítorí wọn fi ohun èlò ìpakà pa Gílíádì.Pẹ̀lú ohun èlo irin tí ó ní eyín mímú
4. Èmi yóò rán iná sí ilé HásáélìÈyí ti yóò jó àwọn ààfin Bẹni-Hádádì run.
5. Èmi yóò ṣẹ́ ọ̀pá ìdáàbú Dámásíkù;Èmi yóò sì pa ọba tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Áfénì runÀti ẹni tí ó di ọ̀pá aládé mú ní Bẹti-Édénì.Àwọn ará a Árámù yóò lọ sí ìgbèkùn sí Kírì,”ni Olúwa wí.
6. Èyí ni ohun tí Olúwa wí:“Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ mẹ́ta Gásà,àní nítorí mẹ́rin,Èmi kò ní yí ìpinnu ìjìyà mi padàGẹ́gẹ́ bí í oníṣòwò ẹrú,ó kó gbogbo àwọn ènìyàn mi ní ìgbékùn.Ó sì tà wọ́n fún Édómù,
7. Èmi yóò rán iná sí ara odi Gásàtí yóò jó gbogbo ààfin rẹ̀ run