1. Nígbà tí Áhásì ọmọ Jótamù ọmọ Hùṣáyà jẹ́ ọba Júdà, ọba Résínì ti Árámù àti Pẹ́kà ọmọ Rẹ̀málíà ọba Ísírẹ́lì gòkè wá láti bá Jérúsálẹ́mù jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
2. Báyìí, a sọ fún ilé Dáfídì pé, “Árámù mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Éfáímù”; fún ìdí èyí, ọkàn Áhásì àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.