12. A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú;bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”
13. Ìwọ tí ó wà lọ́nà jínjìn, gbọ́ ohuntí mo ti ṣe;Ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
14. Èrù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Ṣíhónì;ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́:“Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun?Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú ìjóná àìnípẹ̀kun?”
15. Ẹni tí ó ń rìn lódodotí ó ń sọ ohun tí ó tọ́,tí ó kọ èrè tí ó tibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá,tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀,tí ó di etíi rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàntí ó sì di ojúu rẹ̀ sí àtipète ibi
16. ọkùnrin náà nìyìí tí yóò gbé ní ibi gíga,ẹni tí ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi.A ó máa mú àkàrà rẹ̀ wábẹ́ẹ̀ ni omi kì yóò wọ́n ọn.
17. Ojúu rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.